×

So pe: "Emi ki i se akoko ninu awon Ojise. Emi ko 46:9 Yoruba translation

Quran infoYorubaSurah Al-Ahqaf ⮕ (46:9) ayat 9 in Yoruba

46:9 Surah Al-Ahqaf ayat 9 in Yoruba (اليوربا)

Quran with Yoruba translation - Surah Al-Ahqaf ayat 9 - الأحقَاف - Page - Juz 26

﴿قُلۡ مَا كُنتُ بِدۡعٗا مِّنَ ٱلرُّسُلِ وَمَآ أَدۡرِي مَا يُفۡعَلُ بِي وَلَا بِكُمۡۖ إِنۡ أَتَّبِعُ إِلَّا مَا يُوحَىٰٓ إِلَيَّ وَمَآ أَنَا۠ إِلَّا نَذِيرٞ مُّبِينٞ ﴾
[الأحقَاف: 9]

So pe: "Emi ki i se akoko ninu awon Ojise. Emi ko si mo nnkan ti won maa se fun emi ati eyin. Emi ko tele kini kan ayafi ohun ti Won fi ranse si mi ni imisi. Emi ko si je kini kan bi ko se olukilo ponnbele." won wa labe ijoba awon osebo ninu ilu Mokkah alapon-onle. Won si bere si nii yowo kowo si awon omoleyin Anabi (sollalahu 'alayhi wa sallam). Lasiko naa ipo ole ni awon musulumi wa ninu ilu naa. Ko si ohun t’o wa le fi won lokan bale sinu ’Islam tayo ki Anabi (sollalahu 'alayhi wa sallam) je ki o di mimo fun eni kookan awon omoleyin re pe ijiya ati pipa han awon musulumi ni eemo ifoju-egbo-rin. Mo daju pe ko si Anabi kan ninu awon Anabi Olohun (ahm.s.w.) ti ko mo pe ti o ba je pe itumo ti awon kristieni fun ayah naa l’o ba je ododo “emi ko si mo nnkan ti Allahu maa se fun emi ati eyin” ni iba je agbekale re. Bakan naa ise ti Anabi (sollalahu 'alayhi wa sallam) je faye ko yato si ti awon t’o siwaju re ninu awon Ojise Allahu (ahm.s.w). Bakan naa ayah naa n pe wa sibi iduro sinsin ati atemora lasiko inira awon alaigbagbo

❮ Previous Next ❯

ترجمة: قل ما كنت بدعا من الرسل وما أدري ما يفعل بي ولا, باللغة اليوربا

﴿قل ما كنت بدعا من الرسل وما أدري ما يفعل بي ولا﴾ [الأحقَاف: 9]

Shaykh Abu Rahimah Mikael Aykyuni
Sọ pé: "Èmi kì í ṣe àkọ́kọ́ nínú àwọn Òjíṣẹ́. Èmi kò sì mọ n̄ǹkan tí wọ́n máa ṣe fún èmi àti ẹ̀yin. Èmi kò tẹ̀lé kiní kan àyàfi ohun tí Wọ́n fi ránṣẹ́ sí mi ní ìmísí. Èmi kò sì jẹ́ kiní kan bí kò ṣe olùkìlọ̀ pọ́nńbélé." wọ́n wà lábẹ́ ìjọba àwọn ọ̀ṣẹbọ nínú ìlú Mọkkah alápọ̀n-ọ́nlé. Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí níí yọwọ́ kọ́wọ́ sí àwọn ọmọlẹ́yìn Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam). Lásìkò náà ipò ọ̀lẹ ni àwọn mùsùlùmí wà nínú ìlú náà. Kò sí ohun t’ó wá lè fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀ sínú ’Islām tayọ kí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) jẹ́ kí ó di mímọ̀ fún ẹnì kọ̀ọ̀kan àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé ìjìyà àti pípa han àwọn mùsùlùmí ni èèmọ̀ ìfojú-egbò-rìn. Mọ̀ dájú pé kò sí Ànábì kan nínú àwọn Ànábì Ọlọ́hun (ahm.s.w.) tí kò mọ̀ pé tí ó bá jẹ́ pé ìtúmọ̀ tí àwọn kristiẹni fún āyah náà l’ó bá jẹ́ òdodo “èmi kò sì mọ n̄ǹkan tí Allāhu máa ṣe fún èmi àti ẹ̀yin” ni ìbá jẹ́ àgbékalẹ̀ rẹ̀. Bákan náà iṣẹ́ tí Ànábì (sollalāhu 'alayhi wa sallam) jẹ́ fáyé kò yàtọ̀ sí ti àwọn t’ó ṣíwájú rẹ̀ nínú àwọn Òjíṣẹ́ Allāhu (ahm.s.w). Bákan náà āyah náà ń pè wá síbi ìdúró ṣinṣin àti àtẹ̀mọra lásìkò ìnira àwọn aláìgbàgbọ́
❮ Previous Next ❯

Verse in more languages

Transliteration Bangla Bosnian German English Persian French Hindi Indonesian Kazakh Dutch Russian Spanish Turkish Urdu Uzbek